Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Bible in 90 Days

An intensive Bible reading plan that walks through the entire Bible in 90 days.
Duration: 88 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Hosea 13:7 - Amosi 9:10

Nítorí náà, Èmi yóò dìde sí wọn bí i kìnnìún
    Èmi yóò fi ara pamọ́ dè wọ́n lọ́nà bí i ẹkùn.
Beari igbó tí a já ọmọ rẹ̀ gbà
    Èmi yóò bá wọn jà bí?
Èmi yóò sì fà wọ́n ya
    bí ìgbà tí ẹkùn bá fa ara wọn ya
    bi ẹranko búburú ni èmi yóò fa wọn ya.

“A ti pa ọ́ run, ìwọ Israẹli
    nítorí pé ìwọ lòdì sí mi, ìwọ lòdì sí olùrànlọ́wọ́ rẹ.
10 Níbo ni ọba rẹ gbé wà nísinsin yìí kí ó bá à le gbà ọ là?
    Níbo ni àwọn olórí ìlú yín wà,
àwọn tí ẹ sọ pé,
    ‘Fún wa ní ọba àti ọmọ-aládé’?
11 Nítorí èyí nínú ìbínú mi ni mo fún un yín ní ọba,
    Nínú ìbínú gbígbóná mi, mo sì mú un kúrò.
12 Ẹ̀bi Efraimu ni a tí ko jọ
    gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ wà nínú àkọsílẹ̀
13 Ìrora bí obìnrin tó fẹ́ bímọ ti dé bá a
    Ṣùgbọ́n ó jẹ́ ọmọ tí kò lọ́gbọ́n
Nígbà tí àsìkò tó,
    ó kọ̀ láti jáde síta láti inú.

14 “Èmi yóò rà wọ́n padà kúrò lọ́wọ́ agbára isà òkú.
    Èmi yóò rà wọ́n padà lọ́wọ́ ikú
Ikú, àjàkálẹ̀-ààrùn rẹ dà?
    Isà òkú, ìparun rẹ dà?

“Èmi kò ní ṣàánú mọ́.
15     Bí ó tilẹ̀ gbilẹ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀
afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀dọ̀ Olúwa yóò wá,
    Yóò fẹ́ wá láti inú aginjù
orísun omi rẹ̀ yóò gbẹ
    kànga rẹ̀ yóò gbẹ
pẹ̀lú olè yóò fọ́ ilé ẹrù
    àti gbogbo ilé ìṣúra rẹ̀
16 Ará Samaria gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn,
    nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run wọn.
Wọn ó ti ipa idà ṣubú;
    a ó fọ́ àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀,
    A ó sì la àwọn aboyún wọn nínú.”

Ìwòsàn ń bẹ fún àwọn tó ronúpìwàdà

14 Yípadà ìwọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
    Ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ló fa ìparun rẹ!
(A)Ẹ gba ọ̀rọ̀ Olúwa gbọ́,
    kí ẹ sì yípadà sí Olúwa.
Ẹ sọ fún un pé:
    “Darí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá
kí o sì fi oore-ọ̀fẹ́ gbà wá,
    kí àwa kí ó lè fi ètè wa sán an fún ọ
Asiria kò le gbà wá là;
    A kò ní í gorí ẹṣin ogun
A kò sì ní tún sọ ọ́ mọ́ láé
    ‘Àwọn ni òrìṣà wa
sí àwọn ohun tí ó fi ọwọ́ wa ṣe;
    nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni àwọn
    aláìní baba tí ń rí àánú.’

“Èmi wo àgàbàgebè wọn sàn,
    Èmi ó sì fẹ́ràn wọn, lọ́fẹ̀ẹ́,
    nítorí ìbínú mi ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
Èmi o dàbí ìrì sí Israẹli
    wọn o sì yọ ìtànná bi ewéko lílì
Bi kedari ti Lebanoni yóò si ta gbòǹgbò
    Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà,
Dídán ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi olifi
    Òórùn rẹ yóò sì dàbí igi kedari ti Lebanoni.
Àwọn ènìyàn yóò tún padà gbé lábẹ́ òjijì rẹ̀.
    Yóò rúwé bi ọkà.
Yóò sì yọ ìtànná bi àjàrà,
    òórùn rẹ yóò dàbí ti wáìnì Lebanoni.
Ìwọ Efraimu; Kín ló tún kù tí mo ní ṣe pẹ̀lú ère òrìṣà?
    Èmi ó dá a lóhùn, èmi ó sì ṣe ìtọ́jú rẹ.
Mo dàbí igi junifa tó ń fi gbogbo ìgbà tutù,
    èso tí ìwọ ń so si ń wá láti ọ̀dọ̀ mi.”

(B)Ta ni ọlọ́gbọ́n? Òun yóò mòye àwọn nǹkan wọ̀nyí
    Ta a ní ó mọ̀? Òun yóò ní ìmọ̀ wọn.
Títọ́ ni ọ̀nà Olúwa
    àwọn olódodo si ń rìn nínú wọn
    Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni yóò kọsẹ̀ nínú wọn.

Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Joẹli ọmọ Petueli wá.

Ìṣígun Eṣú

Ẹ gbọ́ èyí ẹ̀yin àgbàgbà;
    ẹ fi etí sílẹ̀ gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ará ilẹ̀ náà.
Ǹjẹ́ irú èyí ha wà ní ọjọ́ yín,
    tàbí ní ọjọ́ àwọn baba yín?
Ẹ sọ ọ́ fún àwọn ọmọ yín,
    ki àwọn ọmọ yín sọ fún àwọn ọmọ wọn,
    ki àwọn ọmọ wọn sọ fún àwọn ìran mìíràn.
Èyí tí eṣú tí agénijẹ jẹ kù
    ní ọ̀wọ́ eṣú ńláńlá ti jẹ,
èyí tí ọ̀wọ́ eṣú ńláńlá jẹ kù
    ní eṣú kéékèèkéé jẹ
Èyí tí eṣú kéékèèkéé jẹ kù
    ni eṣú apanirun mìíràn jẹ.

Ẹ jí gbogbo ẹ̀yin ọ̀mùtí kí ẹ sì sọkún
    ẹ hu gbogbo ẹ̀yin ọ̀mu-wáìnì;
ẹ hu nítorí wáìnì tuntun
    nítorí a gbà á kúrò lẹ́nu yín.
(C)Nítorí orílẹ̀-èdè kan ti ṣígun sí ilẹ̀ mìíràn
    ó ní agbára púpọ̀, kò sì ní òǹkà;
ó ní eyín kìnnìún
    ó sì ní èrìgì abo kìnnìún.
Ó ti pa àjàrà mi run,
    ó sì ti ya ẹ̀ka igi ọ̀pọ̀tọ́ mi kúrò,
ó ti bò èèpo rẹ̀ jálẹ̀, ó sì sọ ọ́ nù;
    àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ni a sì sọ di funfun.

Ẹ pohùnréré ẹkún bí wúńdíá
    tí a fi aṣọ ọ̀fọ̀ dí ni àmùrè, nítorí ọkọ ìgbà èwe rẹ̀.
A ké ọrẹ jíjẹ́ àti ọrẹ mímu kúrò
    ní ilé Olúwa;
àwọn àlùfáà ń ṣọ̀fọ̀, àwọn
    ìránṣẹ́ Olúwa,
10 Oko di ìgboro, ilẹ̀ ń ṣọ̀fọ̀,
    nítorí a fi ọkà ṣòfò:
    ọtí wáìnì tuntun gbẹ, òróró ń bùṣe.

11 Kí ojú kí ó tì yín, ẹ̀yin àgbẹ̀;
    ẹ pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùtọ́jú àjàrà,
nítorí alikama àti nítorí ọkà barle;
    nítorí ìkórè oko ṣègbé.
12 Àjàrà gbẹ, igi ọ̀pọ̀tọ́ sì rọ̀ dànù;
    igi pomegiranate, igi ọ̀pẹ pẹ̀lú,
àti igi apiili, gbogbo igi igbó ni o rọ:
    Nítorí náà ayọ̀ ọmọ ènìyàn gbẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.

Ìpè fún ìrònúpìwàdà

13 Ẹ di ara yín ni àmùrè,
    sí pohùnréré ẹkún ẹ̀yin àlùfáà:
ẹ pohùnréré ẹkún, ẹ̀yin ìránṣẹ́ pẹpẹ:
    ẹ wá, fi gbogbo òru dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀,
ẹ̀yin ìránṣẹ́ Ọlọ́run mi: nítorí tí a dá ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ
    mímu dúró ní ilé Ọlọ́run yín.
14 Ẹ yà àwẹ̀ kan sí mímọ́,
    ẹ pe àjọ kan tí o ní ìrònú,
ẹ pe àwọn àgbàgbà,
    àti gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà
jọ sí ilé Olúwa Ọlọ́run yín,
    kí ẹ sí ké pe Olúwa.

15 A! Fún ọjọ́ náà,
    nítorí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,
    yóò de bí ìparun láti ọwọ́ Olódùmarè.

16 A kò ha ké oúnjẹ kúrò níwájú
    ojú wá yìí,
ayọ̀ àti inú dídùn kúrò nínú ilé
    Ọlọ́run wá?
17 Irúgbìn bàjẹ́ nínú ebè wọn,
    a sọ àká di ahoro, a wó àká palẹ̀;
    nítorí tí a mú ọkà rọ.
18 Àwọn ẹranko tí ń kérora tó!
    Àwọn agbo ẹran dààmú,
nítorí tí wọ́n kò ni pápá oko;
    nítòótọ́, àwọn agbo àgùntàn jìyà.

19 Olúwa, sí ọ ni èmi o ké pè,
    nítorí iná tí run pápá oko tútù aginjù,
    ọwọ́ iná sí ti jó gbogbo igi igbó.
20 Àwọn ẹranko igbó gbé ojú sókè sí ọ pẹ̀lú:
    nítorí tí àwọn ìṣàn omi gbẹ,
    iná sí ti jó àwọn pápá oko aginjù run.

Àwọn jagunjagun eṣú

Ẹ fun ìpè ní Sioni,
    ẹ sì fún ìpè ìdágìrì ní òkè mímọ́ mi.

Jẹ́ kí àwọn ará ilẹ̀ náà wárìrì,
    nítorí tí ọjọ́ Olúwa ń bọ̀ wá,
nítorí ó kù sí dẹ̀dẹ̀.
    Ọjọ́ òkùnkùn àti ìrọ́kẹ̀kẹ̀,
    ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn biribiri,
Bí ọyẹ́ òwúrọ̀ ti í la bo orí àwọn òkè ńlá:
    àwọn ènìyàn ńlá àti alágbára; ya dé,
ti kó ti ì sí irú rẹ̀ rí,
    bẹ́ẹ̀ ni irú rẹ̀ kì yóò sí mọ́ lẹ́yìn rẹ̀, títí dé ọdún ìran dé ìran.

Iná ń jó níwájú wọ́n;
    ọwọ́ iná sì ń jó lẹ́yìn wọn:
Ilẹ̀ náà dàbí ọgbà Edeni níwájú wọn,
    àti lẹ́yìn wọn bí ahoro ijù;
    nítòótọ́, kò sì sí ohun tí yóò bọ́ lọ́wọ́ wọn.
(D)Ìrí wọn dàbí ìrí àwọn ẹṣin;
    wọ́n ń sáré lọ bí àwọn ẹlẹ́ṣin ogun
Bí ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ni
    wọn ń fo ní orí òkè
bí ariwo ọ̀wọ́-iná tí ń jó koríko gbígbẹ,
    bí akọni ènìyàn tí a kójọ fún ogun.

Ní ojú wọn, àwọn ènìyàn yóò jẹ ìrora púpọ̀:
    gbogbo ojú ní yóò ṣú dudu.
Wọn yóò sáré bi àwọn alágbára;
    wọn yóò gùn odi bí ọkùnrin ológun;
olúkúlùkù wọn yóò sì rìn lọ ní ọ̀nà rẹ̀,
    wọn kì yóò sì yà kúrò ni ọ̀nà wọn.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò kọlu ẹnìkejì rẹ̀;
    olúkúlùkù wọn yóò rìn ní ọ̀nà rẹ̀:
nígbà tí wọn bá sì ṣubú lù idà
    wọn kì yóò gbọgbẹ́.
Wọn yóò sáré síwá sẹ́yìn ní ìlú;
    wọn yóò súré lórí odi,
wọn yóò gùn orí ilé;
    wọn yóò gbà ojú fèrèsé wọ̀ inú ilé bí olè.

10 (E)Ayé yóò mì níwájú wọn;
    àwọn ọ̀run yóò wárìrì;
oòrùn àti òṣùpá yóò ṣókùnkùn,
    àwọn ìràwọ̀ yóò sì fà ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn.
11 (F)Olúwa yóò sì bú ramúramù
    jáde níwájú ogun rẹ̀:
nítorí ibùdó rẹ̀ tóbi gidigidi;
    nítorí alágbára ní òun, tí n mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ;
nítorí ọjọ́ Olúwa tóbi ó sì ní ẹ̀rù gidigidi;
    ara ta ni ó lè gbà á?

Fa ọkàn rẹ ya

12 “Ǹjẹ́ nítorí náà nísinsin yìí,” ni Olúwa wí,
    “Ẹ fi gbogbo ọkàn yín yípadà sí mi,
    àti pẹ̀lú àwẹ̀, àti pẹ̀lú ẹkún, àti pẹ̀lú ọ̀fọ̀.”

13 Ẹ sì fa ọkàn yín ya,
    kì í sì í ṣe aṣọ yín,
ẹ sì yípadà sí Olúwa Ọlọ́run yín,
    nítorí tí o pọ̀ ní oore-ọ̀fẹ́,
ó sì kún fun àánú, ó lọ́ra láti bínú,
    ó sì ṣeun púpọ̀, ó sì ronúpìwàdà láti ṣe búburú.
14 Ta ni ó mọ̀ bí òun yóò yípadà, kí o sì ronúpìwàdà,
    kí ó sì fi ìbùkún sílẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀—
àní ọrẹ-jíjẹ àti ọrẹ mímu
    fún Olúwa Ọlọ́run yín?

15 Ẹ fún ìpè ní Sioni,
    ẹ ya àwẹ̀ kan sí mímọ́,
    ẹ pe àjọ tí ó ni ìrònú.
16 Ẹ kó àwọn ènìyàn jọ,
    ẹ ya ìjọ sí mímọ́;
ẹ pe àwọn àgbàgbà jọ,
    ẹ kó àwọn ọmọdé jọ,
    àti àwọn tí ń mú ọmú:
jẹ kí ọkọ ìyàwó kúrò nínú ìyẹ̀wù rẹ̀.
    Kí ìyàwó sì kúrò nínú iyàrá rẹ̀
17 Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, àwọn ìránṣẹ́ Olúwa,
    sọkún láàrín ìloro àti pẹpẹ.
Sí jẹ́ kí wọn wí pé, “Dá àwọn ènìyàn rẹ sí, Olúwa.
    Má sì ṣe fi ìní rẹ fun ẹ̀gàn,
    tí yóò sì di òwe ní àárín àwọn kèfèrí.
Èéṣe tí wọn yóò fi wí láàrín àwọn ènìyàn pé,
    ‘Ọlọ́run wọn ha da?’ ”
18 Nígbà náà ní Olúwa yóò jowú fún ilẹ̀ rẹ̀,
    yóò sì káàánú fún ènìyàn rẹ̀.

19 Nítòótọ́, Olúwa yóò dá wọn lóhùn:

“Yóò sì wí fun àwọn ènìyàn rẹ̀ pé,
    Wò ó èmi yóò rán ọkà, àti ọtí wáìnì tuntun,
àti òróró sí i yín, a ó sì fi wọn tẹ́ yín lọ́rùn:
    èmi kì yóò sì fi yín ṣe ẹ̀gàn mọ́ láàrín àwọn aláìkọlà.

20 “Ṣùgbọ́n èmi yóò lé ogun àríwá jìnnà réré kúrò lọ́dọ̀ yín,
    èmi yóò sì lé e lọ sí ilẹ̀ tí ó ṣá, tí ó sì di ahoro,
pẹ̀lú ojú rẹ̀ sí Òkun ìlà-oòrùn,
    àti ẹ̀yìn rẹ̀ sí ìwọ̀-oòrùn Òkun.
Òórùn rẹ̀ yóò sì gòkè,
    òórùn búburú rẹ̀ yóò sì gòkè.”

Nítòótọ́ ó ti ṣe ohun ńlá.
21     Má bẹ̀rù, ìwọ ilẹ̀;
    jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn kí o sì yọ̀,
nítorí Olúwa ti ṣe ohun ńlá,
22     Ẹ má bẹ̀rù, ẹranko igbó,
    nítorí pápá oko aginjù ń rú,
nítorí igi ń so èso rẹ̀, igi ọ̀pọ̀tọ́
    àti àjàrà ń so èso ọ̀rọ̀ wọn.
23 Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, ẹ̀yin ọmọ Sioni,
    ẹ sì yọ̀ nínú Olúwa Ọlọ́run yín,
nítorí ó ti fi àkọ́rọ̀ òjò fún yín bí ó ti tọ́,
    Òun ti mú kí òjò rọ̀ sílẹ̀ fún un yín,
àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní oṣù kìn-ín-ní.
24 Àwọn ilẹ̀ ìpakà yóò kún fún ọkà;
    àti ọpọ́n wọn nì yóò sàn jáde
    pẹ̀lú ọtí wáìnì tuntun àti òróró.

25 “Èmi yóò sì mú ọdún wọ̀nyí ti eṣú jẹ run padà fún un yín.
    Èyí tí eṣú agénijẹ àti eṣú jewéjewé
    ọwọ́ eṣú agénijẹ àti kòkòrò ajẹnirun mìíràn ti fi jẹ
àwọn ogun ńlá mi tí mo rán sí àárín yín.
26 Ẹ̀yin yóò ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ láti jẹ, títí ẹ̀yin yóò fi yó
    ẹ ó sì yín orúkọ Olúwa Ọlọ́run yín,
ẹni tí ó fi ìyanu bá yín lò;
    ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mi láéláé.
27 Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, èmi wà láàrín Israẹli,
    àti pé; Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín,
    àti pé kò sí ẹlòmíràn:
Ojú kì yóò sì ti àwọn ènìyàn mí láéláé.

Ọjọ́ Olúwa

28 (G)“Yóò sì ṣe níkẹyìn ọjọ́,
    èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí sí ara ènìyàn gbogbo;
àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀,
    àwọn arúgbó yín yóò máa lá àlá,
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò máa ríran.
29 Àti pẹ̀lú sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin,
    àti sí ara àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ obìnrin,
    ní èmi yóò tú ẹ̀mí mí jáde ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì.
30 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn ní ọrun
    àti ní ayé,
    ẹ̀jẹ̀ àti iná, àti ọ̀wọ́n èéfín.
31 (H)A á sọ oòrùn di òkùnkùn,
    àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,
    kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ẹ̀rù Olúwa tó dé.
32 (I)Yóò sí ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó ba ké pè
    orúkọ Olúwa ní a ó gbàlà:
nítorí ní òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu
    ní ìgbàlà yóò gbé wà,
    Olúwa ti wí,
àti nínú àwọn
    ìyókù tí Olúwa yóò pè.

A dá orílẹ̀-èdè lẹ́jọ́

“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, àti ní àkókò náà,
    nígbà tí èmi tún mú ìgbèkùn Juda àti Jerusalẹmu padà bọ̀.
Èmi yóò kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ
    pẹ̀lú èmi yóò sì mú wọn wá sí Àfonífojì Jehoṣafati.
Èmi yóò sì bá wọn wíjọ́ níbẹ̀ nítorí àwọn ènìyàn mi,
    àti nítorí Israẹli ìní mi,
tí wọ́n fọ́nká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè,
    wọ́n sì pín ilẹ̀ mi.
Wọ́n si ti di ìbò fún àwọn ènìyàn mi;
    wọ́n sì ti fi ọmọdékùnrin kan fún panṣágà obìnrin kan,
wọ́n sì ta ọmọdébìnrin kan fún
    ọtí wáìnì, kí wọ́n kí ó lè mu.

(J)“Nísinsin yìí, kí ni ẹ̀yin ní fi mí ṣe Tire àti Sidoni, àti gbogbo ẹ̀yin ẹkún Filistia? Ẹ̀yin yóò ha sàn ẹ̀san fún mi? Bí ẹ̀yin bá sì san ẹ̀san fún mi, ní kánkán àti ní kíákíá ní èmi yóò san ẹ̀san ohun ti ẹ̀yin ṣe padà sórí ara yín. Nítorí tí ẹ̀yin tí mú fàdákà mi àti wúrà mi, ẹ̀yin si tí mú ohun rere dáradára mi lọ sínú tẹmpili yín. Àti àwọn ọmọ Juda, àti àwọn ọmọ Jerusalẹmu ní ẹ̀yin ti tà fún àwọn ará Giriki, kí ẹ̀yin bá à lè sí wọn jìnnà kúrò ní agbègbè ilẹ̀ ìní wọn.

“Kíyèsi í, èmi yóò gbé wọ́n dìde kúrò níbi tì ẹ̀yin ti tà wọ́n sí, èmi yóò sì san ẹ̀san ohun ti ẹ ṣe padà sórí ara yín. Èmi yóò si tà àwọn ọmọkùnrin yín àti àwọn ọmọbìnrin yín sí ọwọ́ àwọn ọmọ Juda, wọ́n yóò sì tà wọ́n fún àwọn ara Sabeani, fún orílẹ̀-èdè kan tí ó jìnnà réré.” Nítorí Olúwa ní o ti sọ ọ.

Ẹ kéde èyí ní àárín àwọn kèfèrí;
    Ẹ dira ogun,
ẹ jí àwọn alágbára,
    Jẹ kí àwọn ajagun kí wọn bẹ̀rẹ̀ ogun,
10 (K)Ẹ fi irin ìtulẹ̀ yín rọ idà,
    àti dòjé yín rọ ọ̀kọ̀.
Jẹ́ kí aláìlera wí pé,
    “Ara mi le koko.”
11 Ẹ wá kánkán, gbogbo ẹ̀yin kèfèrí láti gbogbo àyíká,
    kí ẹ sì gbá ara yín jọ yí káàkiri.

Níbẹ̀ ní kí o mú àwọn alágbára rẹ sọ̀kalẹ̀, Olúwa.

12 “Ẹ jí, ẹ sì gòkè wá sí Àfonífojì
    Jehoṣafati ẹ̀yin kèfèrí:
nítorí níbẹ̀ ní èmi yóò jókòó láti ṣe
    ìdájọ́ àwọn kèfèrí yí káàkiri.
13 Ẹ tẹ dòjé bọ̀ ọ́,
    nítorí ìkórè pọ́n:
ẹ wá, ẹ sọ̀kalẹ̀;
    nítorí ìfúntí kún, nítorí àwọn
    ọpọ́n kún àkúnwọ́sílẹ̀
nítorí ìwà búburú wọn pọ̀!”

14 Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ọ̀pọ̀lọpọ̀
    ní àfonífojì ìpinnu,
nítorí ọjọ́ Olúwa kù si dẹ̀dẹ̀
    ní àfonífojì ìdájọ́.
15 Oòrùn àti òṣùpá yóò ṣú òkùnkùn,
    àti àwọn ìràwọ̀ kí yóò tan ìmọ́lẹ̀ wọn mọ́.
16 Olúwa yóò sí ké ramúramù láti Sioni wá,
    yóò sì fọ ohùn rẹ̀ jáde láti Jerusalẹmu wá;
    àwọn ọ̀run àti ayé yóò sì mì tìtì
Ṣùgbọ́n Olúwa yóò ṣe ààbò àwọn ènìyàn rẹ̀,
    àti agbára àwọn ọmọ Israẹli.

Ìbùkún fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run

17 “Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín,
    tí ń gbé Sioni òkè mímọ́ mi.
Ìgbà náà ni Jerusalẹmu yóò jẹ́ mímọ́;
    àwọn àjèjì kì yóò sì kó o mọ́.

18 “Ní ọjọ́ náà, àwọn òkè ńlá yóò máa kán ọtí wáìnì tuntun sílẹ̀,
    àwọn òkè kéékèèkéé yóò máa sàn fún wàrà;
    gbogbo odò Juda tí ó gbẹ́ yóò máa sàn fún omi.
Orísun kan yóò sì ṣàn jáde láti inú ilé Olúwa wá,
    yóò sì rin omi sí àfonífojì Ṣittimu.
19 Ṣùgbọ́n Ejibiti yóò di ahoro,
    Edomu yóò sì di aṣálẹ̀ ahoro,
nítorí ìwà ipá tí a hù sì àwọn ọmọ Juda,
    ní ilẹ̀ ẹni tí wọ́n ti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.
20 Ṣùgbọ́n Juda yóò jẹ́ ibùgbé títí láé,
    àti Jerusalẹmu láti ìran dé ìran.
21 Nítorí èmi yóò wẹ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn nù, tí èmi kò tí ì wẹ̀nù.

Nítorí Olúwa ń gbé Sioni.”

Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.

(L)Ó wí pé:

Olúwa yóò bú jáde láti Sioni
    ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá;
Ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀,
    orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”

Ìdájọ́ àwọn aládùúgbò Israẹli

(M)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku,
    àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi.
    Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú
Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli
    Èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku;
    Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní Àfonífojì Afeni run
àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni.
    Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,”
    ni Olúwa wí.

(N)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa,
    àní nítorí mẹ́rin,
Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
    Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,
ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn.
    Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa
    tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run
Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò,
    ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú.
Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni
    títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,”
    ni Olúwa Olódùmarè wí.

(O)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire
    àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.
Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu
    Wọn kò sì nání májẹ̀mú ọbàkan,
10 Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire
    Tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”

11 (P)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu,
    àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,
    Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù
ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí
    ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́
12 Èmi yóò rán iná sí orí Temani
    Tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”

13 (Q)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni
    àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi
    kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba
    èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run
pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun,
    pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn
    Òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,”
    ni Olúwa wí.

(R)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu,
    àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà,
Nítorí ó ti sun ún, di eérú,
    egungun ọba Edomu
Èmi yóò rán iná sí orí Moabu
    èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run.
Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo
    pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè
Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò
    Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,”
    ni Olúwa wí.

Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda,
    àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà
Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀
    wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́
Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà
    òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé
Èmi yóò rán iná sí orí Juda
    èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”

Ìdájọ́ tí yóò wá sórí Israẹli

Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli
    àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà.
Wọ́n ta olódodo fún fàdákà
    àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀
    bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀
    tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára
Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà
    Láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́
Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ
    Lórí aṣọ tí wọ́n ti jẹ́ ẹ̀jẹ́
ní ilé òrìṣà wọn
    wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.

“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn
    gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari.
    Òun sì le koko bí igi óákù
mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá
    àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
    mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún
    láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.

11 “Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín
    àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri
èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?”
    ni Olúwa wí.
12 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu
    e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.

13 “Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀
    bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ
    alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀
    jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là
15 Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀
    bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin
    kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là
16 Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ
    yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,”
    ni Olúwa wí.

Ẹ̀rí jíjẹ́ nípa àwọn ọmọ Israẹli

Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:

“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn
    nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí;
nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà
    fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”

Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀
    láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó,
    bí kò bá ní ohun ọdẹ?
Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀
    bí kò bá rí ohun kan mú?
Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀
    nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un?
Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀
    nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú,
    àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù?
Tí ewu bá wa lórí ìlú
    kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?

(S)Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan
    láìfi èrò rẹ̀ hàn
    fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.

Kìnnìún ti bú ramúramù
    ta ni kì yóò bẹ̀rù?
Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀
    ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?

Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu
    àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti.
“Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria;
    Kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀
    àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”

10 “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí,
    “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”

11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run;
    yóò wó ibi gíga yín palẹ̀
    a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”

12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Bí olusọ-àgùntan ti ń gbà itan méjì
    kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan
    bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli,
tí ń gbé Samaria kúrò
    ní igun ibùsùn wọn
    ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”

13 “Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.

14 “Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
    Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run;
ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò
    yóò sì wó lulẹ̀.
15 Èmi yóò wó ilé òtútù
    lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru;
ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé
    a ó sì pa ilé ńlá náà run,”
    ni Olúwa wí.

Israẹli kò yípadà sí Ọlọ́run

Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria,
    ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára,
    tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra:
    “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́
nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ,
    ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ
    gba àárín odi yíya
    a ó sì lé e yín sí Harmoni,”
    ni Olúwa wí.
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀;
    ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i.
Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá,
    ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun
    kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá
lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli,
    nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,”
    ni Olúwa Olódùmarè wí.

“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín,
    àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín,
    síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,”
    ni Olúwa wí.

“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró
    nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta.
Mo rán òjò sí ibùgbé kan
    ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn.
Oko kan ní òjò;
    àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi
    wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,”
    ni Olúwa wí.

“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín
    mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n.
Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

10 “Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín
    bí mo ti ṣe sí Ejibiti.
Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín.
    Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn.
Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

11 “Mo ti bì ṣubú nínú yín,
    bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú
ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

12 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli,
    àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín,
    ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”

13 Ẹni tí ó dá àwọn òkè
    tí ó dá afẹ́fẹ́
    tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn,
ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn
    tí ó sì tẹ ibi gíga ayé.
    Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

Wò mí kí o sì yè

Gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ìwọ ilé Israẹli, ìpohùnréré ẹkún tí mo ṣe nípa rẹ:

“Wúńdíá Israẹli ṣubú
    láì kò sì le padà dìde
ó di ẹni ìkọ̀tì ní ilẹ̀ rẹ̀
    kò sí ẹni tí yóò gbé e dìde.”

Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí:

“Ìlú tí ẹgbẹ̀rún alágbára ti jáde,
    yóò dín ku ọgọ́ọ̀rún ní Israẹli.
Ìlú tí ọgọ́ọ̀rún alàgbà ti jáde
    yóò ṣẹ́kù ẹni mẹ́wàá.”

Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ilé Israẹli:

“Wá mi kí o sì yè;
    Ẹ má ṣe wá Beteli,
Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali
    Ẹ má ṣe rìnrìn àjò lọ sí Beerṣeba.
Nítorí dájúdájú a ó kó Gilgali ní ìgbèkùn
    A ó sì sọ Beteli di asán.”
Ẹ wá Olúwa, ẹ̀yin yóò sì yè,
    kí ó má ba à gbilẹ̀ bí iná ní Josẹfu
a sì jó o run
    Beteli kò sì ní rí ẹni tí yóò bu omi pa á.

Ẹ̀yin tí ẹ̀ sọ òdodo di ìkorò
    tí ẹ sì gbé olódodo ṣánlẹ̀.

Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Pleiadesi àti Orioni
    ẹni tí ó sọ òru dúdú di òwúrọ̀
    tí ó sọ ọjọ́ dúdú di ìmọ́lẹ̀
ẹni tí ó wọ́ omi Òkun jọ pọ̀
    tí ó sì rọ̀ wọ́n sí orí ilẹ̀
    Olúwa ni orúkọ rẹ̀,
Ó fọ́n ìparun sí ìlú olódi
    tí ó sì sọ àwọn ibùgbé àwọn ọmọ-aládé di ahoro.

10 Ìwọ kórìíra ẹni tí ń bá ni wí ní ẹnu ibodè
    ó sì ń pẹ̀gàn ẹni tí ń sọ òtítọ́.

11 Ìwọ ń tẹ tálákà mọ́lẹ̀
    o ń fi ipá gba ọkà lọ́wọ́ wọn
Nítorí náà, ìwọ ti fi òkúta tí a gbẹ́ kọ́lé
    ṣùgbọ́n ẹ kò sì ní gbé inú wọn
Nítòótọ́ ìwọ ti gbin ọgbà àjàrà tí ó lẹ́wà.
    Ìwọ kò ní mu wáìnì inú wọn
12 Nítorí mo mọ iye àìṣedéédéé rẹ
    mo sì mọ bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tí tóbi tó.

Ìwọ ni olódodo lára, ìwọ sì ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀
    o sì ń fi òtítọ́ du tálákà ní ilé ẹjọ́
13 Àwọn ọlọ́gbọ́n máa ń dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní àkókò wọ̀nyí,
    nítorí búburú ni gbogbo ọjọ́.

14 Wá rere, má ṣe wá búburú
    kí ìwọ ba à le yè
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun yóò wà pẹ̀lú rẹ.
    Òun yóò sì wà pẹ̀lú rẹ bí ìwọ ṣe wí
15 Kórìíra búburú kí o sì fẹ́ rere
    dúró ní orí òtítọ́ ní ilé ẹjọ́
bóyá Olúwa Ọlọ́run alágbára
    yóò ṣíjú àánú wo ọmọ Josẹfu tó ṣẹ́kù.

16 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí:

“Ẹkún yóò wà ní àwọn òpópónà
    igbe ìnira yóò sì wà ní àwọn gbàgede ìlú
A ó kó àwọn àgbẹ̀ jọ láti sọkún
    àti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ láti pohùnréré ẹkún
17 Ìpohùnréré ẹkún yóò wà ní gbogbo ọgbà àjàrà
    Nítorí èmi yóò la àárín yín kọjá,”
    ni Olúwa wí.

Ọjọ́ Olúwa

18 Ègbé ni fún ìwọ tí ó pẹ́
    nítorí ọjọ́ Olúwa
kí ni ìwọ fi pẹ́ fún ọjọ́ Olúwa?
    Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn ní ojú ọjọ́
19 Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ó sá fún kìnnìún,
    tí ó padà wá bọ́ sí ẹnu àmọ̀tẹ́kùn.
Yóò dàbí ẹni tí ó wọ ilé rẹ̀ lọ
    tí ó sinmi lé ògiri ilé rẹ̀
    tí ejò sì bù ú ṣán.
20 Ǹjẹ́ ọjọ́ Olúwa kò ha ní ṣókùnkùn dípò kí ó ní ìmọ́lẹ̀?
    Tí yóò sì ṣókùnkùn dúdú láìsí ìmọ́lẹ̀ kankan níbẹ̀.

21 “Mo kórìíra, mo kẹ́gàn àwọn àsè ẹ̀sìn in yín
    Èmi kò sì ní inú dídùn sí àpéjọ yín
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wá
    Èmi kò ní tẹ́wọ́ gbà wọ́n
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú àṣàyàn ọrẹ àlàáfíà wá.
    Èmi kò ní náání wọn.
23 Ẹ gbé ariwo orin yín sẹ́yìn
    Èmi kò ní fetísí ohun èlò orin yín.
24 Jẹ́ kí òtítọ́ sàn bí odò
    àti òdodo bí ìsun tí kò lé è gbẹ!

25 (T)“Àbí ẹ̀yin mú ẹbọ àti ọrẹ tọ̀ mí wá
    ní ogójì ọdún ní aginjù ìwọ ilé Israẹli?
26 Ẹ̀yin ti gbé ibi ìrúbọ àwọn ọba yín sókè
    ibùgbé àwọn òrìṣà yín
    àní, ti àwọn òrìṣà yín tí ó níyì jùlọ,
    èyí tí ẹ̀yin fi ọwọ́ ara yín ṣe.
27 Nítorí náà èmi yóò rán an yín lọ sí ìgbèkùn ní ìkọjá Damasku,”
    ni Olúwa wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ọlọ́run alágbára.

Ègbé ni fún àwọn tí ara rọ̀

Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni
    àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria
àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè
    tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá
Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó
    kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì.
    Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini
Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ?
    Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú,
    ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí
Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe
    ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn
ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ
    ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ
Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi
    ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin
Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan
    àti ìkunra tí o dára jùlọ
    ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro
Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn
    pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn
àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.

Olúwa Kórìíra Ìgbéraga Ọmọ Israẹli

Olúwa Olódùmarè ti búra fúnrarẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé:

“Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu
    n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀
Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́
    àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”

Bí Ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú 10 Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”

11 Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà,
    Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú
    Àti àwọn ilé kéékèèkéé sí wẹ́wẹ́.

12 Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí?
    Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀?
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé
    ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
13 Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari
    Ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”

14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé,
    “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli,
wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà,
    láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”

Eṣú, iná àti ìwọ̀n okùn

Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀. Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”

Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí.

“Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.

Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run. Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”

Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí.

“Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.

Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀. Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?”

Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.”

Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.

“Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro
    àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro.
    Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”

Amosi àti Amasiah

10 Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀. 11 Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ:

“ ‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú,
    Lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn,
    jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’ ”

12 Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀. 13 Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”

14 Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore. 15 Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’ 16 Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé,

“ ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli
    Má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’

17 “Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí:

“ ‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú,
    àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú.
A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in
    àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́.
Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn,
    kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’ ”

Agbọ̀n èso pípọ́n

Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n. Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.”

Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.”

Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”

Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”

Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba,
    tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.

Tí ẹ ń wí pé,

“Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí
    kí àwa bá à lè ta ọkà
kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin
    kí àwa bá à le ta jéró?”
Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù
    kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á
    kí a sì fi òṣùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ
Kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà
    kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní
    kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.

Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé: “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.

“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí?
    Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀?
Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili,
    yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi
    a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.

“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí,

“Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán,
    Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀,
    gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún.
Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀,
    kí a sì fá orí yín.
Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin
    kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.

11 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí,
    “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà,
kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi.
    Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun
    wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá,
wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa
    ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.

13 “Ní ọjọ́ náà

“àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin
    yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra,
    tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’
    Bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba
Wọ́n yóò ṣubú,
    Wọn kì yóò si tún dìde mọ.”

A o pa Israẹli run

Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé:

“Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn
    kí àwọn òpó kí ó lè mì
fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn
    àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa,
Ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé
    Ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.
Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú
    Láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n
Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ,
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀.
Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli,
    èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀.
Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun,
    láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.
Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa.

“Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí,
    kì í sì í ṣe fún rere.”

Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀;
gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili
    tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.
Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run
    ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé
Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun
    ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé
    Olúwa ni orúkọ rẹ̀.

“Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli
    kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?”
    ni Olúwa wí.
“Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá
    àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori
    àti àwọn ará Aramu láti Kiri?

“Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè
    ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀.
Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀
    Síbẹ̀ Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,”
    ni Olúwa wí.
“Nítorí Èmi yóò pàṣẹ,
    Èmi yóò sì mi ilé Israẹli
    ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè
bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀
    tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
10 Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi
    ni yóò ti ipa idà kú
gbogbo àwọn ti ń wí pé,
    ‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.