Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Bible in 90 Days

An intensive Bible reading plan that walks through the entire Bible in 90 days.
Duration: 88 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Amosi 9:11 - Nahumu 3:19

Ìmúpadàbọ̀ Israẹli

11 (A)“Ní ọjọ́ náà ní
    Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró,
Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya,
    Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè,
    Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,
12 kí wọn le jogún ìyókù Edomu
    àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,”
    ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.

13 (B)“Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí,

“tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá
    Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá
Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀
    Tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèkéé.
14     Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀.

“Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn
    Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn
    wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn
15 Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀.
    A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé
    kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,”

ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.

Ìran ti Ọbadiah.

(C)Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu.

Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá:
    A sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé,
“Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”

“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí;
    ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọpọ̀,
Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ,
    ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta,
    tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga,
ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé,
    ‘ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’
Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì,
    bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀,
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,”
    ni Olúwa wí.
“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá,
    bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru,
Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́:
    wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́?
Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá,
    wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?
Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau,
    tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.
Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ
    ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ:
Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ;
    àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́,
    ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”

Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà,
    Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run,
    àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?
A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, Ìwọ Temani,
    gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau
    ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.
10 Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ,
    ìtìjú yóò bò ọ,
    a ó sì pa ọ run títí láé.
11 Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan,
    ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ,
tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ
    tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu,
    ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.
12 Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ,
    ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀
ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda,
    ní ọjọ́ ìparun wọn
ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀
    ní ọjọ́ wàhálà wọn.
13 Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ,
    ní ọjọ́ àjálù wọn.
Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀
    nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn.
Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó,
    ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14 Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà
    láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò.
Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú
    wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.

15 “Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé
    lórí gbogbo àwọn kèfèrí.
Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà;
    ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.
16 Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi
    bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí
Wọn yóò mu wọn yóò sì mu àmutẹ́rùn
    wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí
17 Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni
    Wọn yóò sì jẹ́ mímọ́
àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn
18 Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná
    àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná
ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko
    wọn yóò fi iná sí i,
wọn yóò jo run.
    Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.”
Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.

19 Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau,
    àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni
ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní.
    Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria;
    Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.
20 Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani
    yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati;
àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi
    yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní
21 Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá
    láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau.
    Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

Jona sá ní iwájú Olúwa

Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona ọmọ Amittai wá, wí pé: “Dìde lọ sí ìlú ńlá Ninefe kí o sì wàásù sí i, nítorí ìwà búburú rẹ̀ gòkè wá iwájú mi.”

Ṣùgbọ́n Jona dìde kúrò láti sálọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Joppa, ìbí ti ó tí rí ọkọ̀ kan tí ń lọ sí Tarṣiṣi: lẹ́yìn ti ó sanwó ọkọ̀, ó wọlé sínú rẹ̀, láti bá wọn lọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa.

Nígbà náà ni Olúwa rán ìjì ńlá jáde sí ojú Òkun, ìjì líle sì wà nínú Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ̀ náà dàbí ẹni pé yóò fọ́. Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ bẹ̀rù, olúkúlùkù sì ń kígbe sí ọlọ́run rẹ̀, wọ́n kó ẹrù tí ó wà nínú ọkọ̀ dà sínú Òkun, kí ó bá à lè fúyẹ́.

Ṣùgbọ́n Jona sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ọkọ̀ ó sì dùbúlẹ̀, ó sùn wọra. Bẹ́ẹ̀ ni olórí ọkọ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi sùn, ìwọ olóòórùn? Dìde kí o ké pe Ọlọ́run rẹ! Bóyá yóò ro tiwa, kí àwa má ba à ṣègbé.”

Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ sọ fún ara wọn pé, “Wá, ẹ jẹ́ kí a sẹ́ kèké, kí àwa kí o le mọ̀ nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa.” Wọ́n ṣẹ́ kèké, kèké sì mú Jona. Nígbà náà ni wọn wí fún un pé, “Sọ fún wa, àwa bẹ̀ ọ́, nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa? Kí ni iṣẹ́ rẹ? Níbo ni ìwọ ti wá? Kí ni orúkọ ìlú rẹ? Ẹ̀yà orílẹ̀-èdè wo sì ni ìwọ sì í ṣe?”

Òun sì dá wọn lóhùn pé, “Heberu ni èmi, mo sì bẹ̀rù Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run ẹni tí ó dá Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀.”

10 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù gidigidi, wọn sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣe èyí?” (Nítorí àwọn ọkùnrin náà mọ̀ pé ó ń sá kúrò ní iwájú Olúwa ni, nítorí òun ti sọ fun wọn bẹ́ẹ̀.)

11 Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Kí ni kí àwa ó ṣe sí ọ kí Òkun lè dákẹ́ fún wa?” Nítorí Òkun ru, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle.

12 Òun sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé mi, kí ẹ sì sọ mi sínú Òkun, bẹ́ẹ̀ ni okun yóò sì dákẹ́ fún un yin. Nítorí èmi mọ̀ pé, nítorí mi ni ẹ̀fúùfù líle yìí ṣe dé bá a yín.”

13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà gbìyànjú gidigidi láti mú ọkọ̀ wà sí ilẹ̀: ṣùgbọ́n wọn kò lè ṣe é: nítorí tí Òkun túbọ̀ ru sí i, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle sí wọn. 14 Nítorí náà wọ́n kígbe sí Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Olúwa àwa bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí àwa ṣègbé nítorí ẹ̀mí ọkùnrin yìí. Má sì ka ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sí wa ní ọrùn, nítorí ìwọ, Olúwa, ti ṣe bí ó ti wù ọ́.” 15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé Jona, tí wọ́n sì sọ ọ́ sínú Òkun, Òkun sì dẹ́kun ríru rẹ̀. 16 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù Olúwa gidigidi, wọn si rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì jẹ́ ẹ̀jẹ́.

17 Ṣùgbọ́n Olúwa ti pèsè ẹja ńlá kan láti gbé Jona mì. Jona sì wà nínú ẹja náà ni ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta.

Àdúrà Jona

Nígbà náà ni Jona gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ láti inú ẹja náà wá, Ó sì wí pé:

“Nínú ìpọ́njú mi ni mo kígbe sí Olúwa,
    òun sì gbọ́ ohùn mi.
Mo kígbe láti inú ipò òkú, mo pè fún ìrànwọ́,
    ìwọ sì gbọ́ ohùn mi.
Nítorí tí ìwọ ti sọ mí sínú ibú,
    ní àárín Òkun,
    ìṣàn omi sì yí mi káàkiri;
gbogbo bíbì omi àti rírú omi
    rékọjá lórí mi.
Nígbà náà ni mo wí pé,
    ‘a ta mí nù kúrò níwájú rẹ;
ṣùgbọ́n síbẹ̀ èmi yóò tún
    máa wo ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ.’
Omi yí mi káàkiri, àní títí dé ọkàn;
    ibú yí mi káàkiri,
    a fi koríko odò wé mi lórí.
Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ àwọn òkè ńlá;
    ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ìdènà rẹ̀ yí mi ká títí:
ṣùgbọ́n ìwọ ti mú ẹ̀mí mi wá sókè láti inú ibú wá,
    Olúwa Ọlọ́run mi.

“Nígbà tí ó rẹ ọkàn mi nínú mi,
    èmi rántí rẹ, Olúwa,
àdúrà mi sì wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,
    nínú tẹmpili mímọ́ rẹ.

“Àwọn tí ń fàmọ́ òrìṣà èké
    kọ àánú ara wọn sílẹ̀.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi orin ọpẹ́, rú ẹbọ sí ọ.
    Èmi yóò san ẹ̀jẹ́ tí mo ti jẹ́.
    ‘Ìgbàlà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.’ ”

10 Olúwa sì pàṣẹ fún ẹja náà, ó sì pọ Jona sí orí ilẹ̀ gbígbẹ.

Jona lọ si Ninefe

Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona wá nígbà kejì wí pé: “Dìde lọ sí Ninefe, ìlú ńlá a nì, kí o sì kéde sí i, ìkéde tí mo sọ fún ọ.”

Jona sì dìde ó lọ sí Ninefe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa. Ninefe jẹ́ ìlú títóbi gidigidi, ó tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jona sì bẹ̀rẹ̀ sí wọ ìlú náà lọ ní ìrìn ọjọ́ kan, ó sì ń kéde, ó sì wí pé, “Níwọ́n ogójì ọjọ́ sí i, a ó bi Ninefe wó.” Àwọn ènìyàn Ninefe sì gba Ọlọ́run gbọ́. Wọ́n sì kéde àwẹ̀, gbogbo wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, bẹ̀rẹ̀ láti orí ọmọdé títí dé orí àgbà wọn.

Ọ̀rọ̀ náà sì dé ọ̀dọ̀ ọba Ninefe, ó sì dìde kúrò lórí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì bọ́ aṣọ ìgúnwà rẹ̀ kúrò lára rẹ̀, ó sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì jókòó nínú eérú. Nígbà náà ní ó kéde rẹ̀ ni Ninefe pé:

“Kí a la Ninefe já nípa àṣẹ ọba, àti àwọn àgbàgbà rẹ̀ pé:

“Má ṣe jẹ́ kí ènìyàn, tàbí ẹranko, ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran, tọ́ ohunkóhun wò: má jẹ́ kí wọn jẹ tàbí mu omi. Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn àti ẹranko da aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, kí wọn sì kígbe kíkan sí Ọlọ́run, sì jẹ́ kí wọn yípadà, olúkúlùkù kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀ àti kúrò ní ìwà ìpa tí ó wà lọ́wọ́ wọn. (D)Ta ni ó lè mọ̀ bí Ọlọ́run yóò yípadà kí ó sì ronúpìwàdà, kí ó sì yípadà kúrò ní ìbínú gbígbóná rẹ̀, kí àwa má ṣègbé?”

10 Ọlọ́run sì rí ìṣe wọn pé wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀nà ibi wọn: Ọlọ́run sì ronúpìwàdà ibi tí òun ti wí pé òun yóò ṣe sí wọn, òun kò sì ṣe e mọ́.

Jona bínú sí àánú tí Olúwa fihàn

Ṣùgbọ́n ó ba Jona nínú jẹ́ gidigidi, ó sì bínú púpọ̀. (E)Ó sì gbàdúrà sí Olúwa, ó sì wí pé, “Èmí bẹ̀ ọ́, Olúwa, ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ ti mo sọ kọ́ ni èyí nígbà tí mo wà ní ilẹ̀ mi? Nítorí èyí ni mo ṣé sálọ sí Tarṣiṣi ní ìṣáájú: nítorí èmi mọ̀ pé, Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ ní ìwọ, àti aláàánú, O lọ́ra láti bínú, O sì ṣeun púpọ̀, O sì ronúpìwàdà ibi náà. Ǹjẹ́ báyìí, Olúwa, èmi bẹ̀ ọ, gba ẹ̀mí mi kúrò lọ́wọ́ mi nítorí ó sàn fún mi láti kú ju àti wà láààyè lọ.”

Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ìwọ́ ha ni ẹ̀tọ́ láti bínú bí?”

Jona sì jáde kúrò ní ìlú náà, ó sì jókòó níhà ìlà-oòrùn ìlú náà. Ó sì pa àgọ́ kan níbẹ̀ fún ara rẹ̀, ó sì jókòó ni òjìji ní abẹ́ rẹ̀ títí yóò fi rí ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ìlú náà. Olúwa Ọlọ́run sì pèsè ìtàkùn kan, ó ṣe é kí ó gòkè wá sórí Jona; kí ó lè ṣe ìji bò ó lórí; láti gbà á kúrò nínú ìbànújẹ́ rẹ̀. Jona sì yọ ayọ̀ ńlá nítorí ìtàkùn náà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run pèsè kòkòrò kan nígbà tí ilẹ̀ mọ́ ní ọjọ́ kejì, ó sì jẹ ìtàkùn náà ó sì rọ. Ó sì ṣe, nígbà tí oòrùn yọ, Ọlọ́run pèsè ẹ̀fúùfù gbígbóná tí ìlà-oòrùn; oòrùn sì pa Jona lórí tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi rẹ̀ ẹ́. Ó sì fẹ́ nínú ara rẹ̀ láti kú, ó sì wí pé, “Ó sàn fún mi láti kú ju àti wà láààyè lọ.”

Ọlọ́run sì wí fún Jona pé, “O ha tọ́ fún ọ láti bínú nítorí ìtàkùn náà?”

Òun sì wí pé, “Mo ni ẹ̀tọ́, o tọ́ fún mi láti bínú títí dé ikú.”

10 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ìwọ kẹ́dùn ìtàkùn náà, nítorí èyí tí ìwọ kò ṣiṣẹ́ fun, tí ìwọ kò mu dàgbà; tí ó hù jáde ní òru kan tí ó sì kú ni òru kan. 11 Ṣùgbọ́n Ninefe ní jù ọ̀kẹ́ mẹ́fà (12,000) ènìyàn nínú rẹ̀, tí wọn kò mọ ọwọ́ ọ̀tún wọn yàtọ̀ sí ti òsì, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọ̀sìn pẹ̀lú. Ṣé èmí kò ha ní kẹ́dùn nípa ìlú ńlá náà?”

Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.

Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,
    fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,
Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín,
    (F)Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.

Ìdájọ́ tí o lòdì sí Samaria àti Jerusalẹmu

Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;
    yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,
    àwọn Àfonífojì yóò sì pínyà,
bí idà níwájú iná,
    bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí,
    àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli.
Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu?
    Ǹjẹ́ Samaria ha kọ?
Kí ni àwọn ibi gíga Juda?
    Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?

“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá,
    bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà.
Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì.
    Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́
    gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun:
    Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run.
Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà,
    gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”

Ẹkún òun ọfọ̀

Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún,
    èmi yóò sì pohùnréré ẹkún:
èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò
    Èmi yóò ké bí akátá,
    èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán;
    ó sì ti wá sí Juda.
Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi,
    àní sí Jerusalẹmu.
10 Ẹ má ṣe sọ ní Gati
    ẹ má ṣe sọkún rárá.
Ní ilẹ̀ Beti-Ofra
    mo yí ara mi nínú eruku.
11 Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú,
    ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri.
Àwọn tí ó ń gbé ni Ṣaanani
    kì yóò sì jáde wá.
Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀;
    A ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre,
    Ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 Ìwọ olùgbé Lakiṣi,
    dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára.
Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀
    sí àwọn ọmọbìnrin Sioni,
    nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀
    fún Moreṣeti Gati.
Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa.
    Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli
    yóò sì wá sí Adullamu.
16 Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀
    nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára,
sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún,
    nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

Èrò ènìyàn àti ti Ọlọ́run

Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé
    tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn!
Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde
    nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n,
    àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n.
Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára
    àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.

Nítorí náà, Olúwa wí pé:

“Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí,
    nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là.
Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́,
    nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín;
    wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé:
‘Ní kíkó a ti kó wọn tán;
    Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi;
Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi!
    Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’ ”

Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa,
    tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.

Àwọn wòlíì èké

“Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn Wòlíì wọn wí.
    “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí;
    kí ìtìjú má ṣe le bá wa”
Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu:
    “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí?
    Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?”

“Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere
    fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde
    bí ọ̀tá sí mi.
Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀
    kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu,
    bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi
    kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn,
ẹ̀yin sì ti gba ògo mi,
    kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ!
    Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín,
nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́
    yóò pa yín run,
    àní ìparun kíkorò.
11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé,
    ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’
    òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!

Ìlérí ìgbàlà

12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu;
    Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ.
Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran,
    gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn,
    ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn;
    wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ.
Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn,
    Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”

Bíbá àwọn olórí àti àwọn wòlíì wí

Nígbà náà, ni mo wí pé,

“Ẹ gbọ́, ẹ̀yin olórí Jakọbu,
    ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli.
Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò ha ni í gba òdodo bí.
    Ẹ̀yin tí ó kórìíra ìre, tí ẹ sì fẹ́ràn ibi;
Ẹ̀yin tí ẹ fa awọ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi ya kúrò lára wọn
    àti ẹran-ara wọn kúrò ní egungun wọn;
Àwọn tí ó jẹ ẹran-ara àwọn ènìyàn mi,
    wọn sì bọ́ awọ ara wọn kúrò lára wọn.
    Wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;
Wọn sì gé e sí wẹ́wẹ́ bí ẹran inú ìkòkò,
    bí ẹran inú agbada?”

Nígbà náà ni wọn yóò kígbe sí Olúwa,
    Ṣùgbọ́n òun kì yóò dá wọn lóhùn.
Ní àkókò náà ni òun yóò fi ojú rẹ̀ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ wọn,
    nítorí ibi tí wọ́n ti ṣe.

Báyìí ni Olúwa wí:

“Ní ti àwọn Wòlíì
    tí ń ṣi àwọn ènìyàn mi lọ́nà,
tí ẹnìkan bá fún wọn ní oúnjẹ,
    wọn yóò kéde àlàáfíà;
Ṣùgbọ́n tí kò bá fi nǹkan sí wọn ní ẹnu,
    wọn yóò múra ogun sí i.
Nítorí náà òru yóò wá sórí yín,
    tí ẹ̀yin kì yóò sì rí ìran kankan,
òkùnkùn yóò sì kùn fún yín,
    tí ẹ̀yin kì yóò sì lè sọtẹ́lẹ̀
Oòrùn yóò sì wọ lórí àwọn wòlíì
    ọjọ́ yóò sì ṣókùnkùn lórí wọn.
Ojú yóò sì ti àwọn Wòlíì
    àwọn alásọtẹ́lẹ̀ pẹ̀lú yóò sì gba ìtìjú.
Gbogbo wọn ni yóò bo ojú wọn,
    nítorí kò sí ìdáhùn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Ṣùgbọ́n ní tèmi,
    èmi kún fún agbára pẹ̀lú ẹ̀mí Olúwa,
    láti sọ ìré-òfin-kọjá Jakọbu fún un,
    àti láti sọ ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli fún un.

Gbọ́ ẹ̀yin olórí ilé Jakọbu,
    àti ẹ̀yin alákòóso ilé Israẹli,
tí ó kórìíra òdodo
    tí ó sì yí òtítọ́ padà;
10 Tí ó kọ́ Sioni pẹ̀lú ìtàjẹ̀ sílẹ̀,
    àti Jerusalẹmu pẹ̀lú ìwà búburú.
11 Àwọn olórí rẹ̀ ń ṣe ìdájọ́ nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀,
    àwọn àlùfáà rẹ̀ sì ń kọ́ni nítorí owó ọ̀yà
    àwọn wòlíì rẹ̀ pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ nítorí owó.
Síbẹ̀, wọn gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, wọ́n sì wí pé,
    “Nítòótọ́, Olúwa wà pẹ̀lú wa!
    Ibi kan kì yóò bá wa.”
12 Nítorí náà, nítorí tiyín,
    ni a ó ṣe ro Sioni bí oko,
Jerusalẹmu yóò sì di ebè
    àti òkè tẹmpili bí i ibi gíga igbó.

Òkè Olúwa

(G)Ní ọjọ́ ìkẹyìn

a ó fi òkè ilé Olúwa lélẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá,
    a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèkéé lọ,
    àwọn ènìyàn yóò sì máa wọ̀ sínú rẹ̀.

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò wá,

wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa,
    àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu
Òun yóò sì kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,
    kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.”
Òfin yóò jáde láti Sioni wá,
    àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn,
    yóò sì parí aáwọ̀ fún orílẹ̀-èdè alágbára jíjìn réré.
Wọn yóò sì fi idà wọn rọ ohun èlò ìtulẹ̀
    àti ọ̀kọ̀ wọn di dòjé
orílẹ̀-èdè kì yóò gbé idà sókè sí orílẹ̀-èdè mọ́,
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
(H)Ṣùgbọ́n olúkúlùkù yóò jókòó lábẹ́ àjàrà rẹ̀
    àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀,
ẹnìkan kì yóò sì dẹ́rùbà wọ́n,
    nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ̀rọ̀.
Gbogbo àwọn ènìyàn ń rìn,
    olúkúlùkù ni orúkọ ọlọ́run tirẹ̀,
ṣùgbọ́n àwa yóò máa rìn ní orúkọ Olúwa.
    Ọlọ́run wa láé àti láéláé.

Èrò Olúwa

“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Èmi yóò kó àwọn arọ jọ;
    èmi yóò sì ṣà àwọn tí a lé kúrò ní ìlú jọ,
    àti àwọn ẹni tí èmi ti pọ́n lójú.
Èmi yóò dá àwọn arọ sí fún èyí tókù,
    èmi yóò sì sọ àwọn tí a lé kúrò ní ìlú di orílẹ̀-èdè alágbára.
Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí wọn ní òkè ńlá Sioni
    láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.
Ní ti ìwọ, ilé ìṣọ́ agbo àgùntàn,
    odi alágbára ọmọbìnrin Sioni,
a ó mú ìjọba ìṣáájú padà bọ̀ sípò fún un yín;
    ìjọba yóò sì wà sí ọ̀dọ̀ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.”

Kí ni ìwọ ha ń kígbe sókè sí nísinsin yìí?
    Ǹjẹ́ ìwọ kò ní ọba bí?
Àwọn ìgbìmọ̀ rẹ ṣègbé bí?
    Nítorí ìrora ti dì ọ́ mú bí obìnrin tí ń rọbí.
10 Máa yí síhìn-ín sọ́hùn-ún nínú ìrora,
    ìwọ obìnrin Sioni,
bí ẹni tí ń rọbí,
    nítorí nísinsin yìí ìwọ yóò jáde lọ kúrò ní ìlú,
ìwọ yóò sì máa gbé inú igbó.
    Ìwọ yóò lọ sí Babeli;
níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì ti rí ìgbàlà.
    Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ.

11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè kó ara wọn jọ sí ọ.
    Wọ́n sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ ọ́ di àìmọ́,
    Ẹ jẹ́ kí ojú wa kí ó wo Sioni!”
12 Ṣùgbọ́n wọn kò mọ
    èrò inú Olúwa;
Bẹ́ẹ̀ ni òye ìmọ̀ rẹ̀ kò yé wọn,
    nítorí ó ti kó wọn jọ bí i ìtí sínú ìpakà.
13 “Dìde, kí ó sì máa pa ọkà ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
    nítorí èmi yóò sọ ìwo rẹ̀ di irin,
èmi yóò sì sọ pátákò rẹ̀ di idẹ
    ìwọ yóò run ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè pátápátá.”
Èmi yóò sì ya èrè wọn sọ́tọ̀ fún Olúwa
    àti ọrọ̀ wọn sí Olúwa gbogbo ayé.

Àsọtẹ́lẹ̀ nípa Olùgbàlà láti Bẹtilẹhẹmu

Nísinsin yìí, kó àwọn ọ̀wọ́ ogun rẹ jọ,
    ìwọ ìlú ti o ni ọmọ-ogun,
nítorí ó ti fi gbógun dó tì wá.
    Wọn yóò fi ọ̀pá lu àwọn alákòóso Israẹli ní ẹ̀rẹ̀kẹ́.

“Ṣùgbọ́n ìwọ, Bẹtilẹhẹmu Efrata,
    bí ìwọ ti jẹ́ kékeré láàrín àwọn ẹ̀yà Juda,
nínú rẹ ni ẹni tí yóò jẹ́ olórí ní Israẹli
    yóò ti jáde tọ̀ mí wá,
ìjáde lọ rẹ̀ sì jẹ́ láti ìgbà àtijọ́,
    láti ìgbà láéláé.”

Nítorí náà Israẹli yóò di kíkọ̀sílẹ̀ pátápátá
    títí di àkókò tí ẹni tí ń rọbí yóò fi bí,
àti àwọn ìyókù arákùnrin rẹ̀ yóò fi padà
    láti darapọ̀ mọ́ àwọn Israẹli.

Òun yóò sì dúró,
    yóò sì máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn àwọn agbo ẹran rẹ̀ ní agbára Olúwa,
    ní ọláńlá orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Wọn yóò sì wà láìléwu,
    nítorí nísinsin yìí ni títóbi rẹ
    yóò sì dé òpin ayé.

Ìgbàlà àti ìparun

Òun yóò sì jẹ́ àlàáfíà wọn.
    Nígbà tí àwọn Asiria bá gbógun sí ilẹ̀ wa
    tí wọ́n sì ń yan lórí odi alágbára wa,
nígbà náà ni a ó gbé olùṣọ́-àgùntàn méje dìde sí i,
    àti olórí ènìyàn mẹ́jọ.
Wọn yóò sì fi idà pa ilẹ̀ Asiria run,
    àti ilẹ̀ Nimrodu pẹ̀lú idà tí a fà.
Òun yóò sì gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Asiria
    nígbà tí wọn bá gbógun ti ilẹ̀ wa
    tí wọ́n sì tún yan wọ ẹnu-bodè wa.

Ìyókù Jakọbu yóò sì wà
    láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn
bí ìrì láti ọ̀dọ̀ Olúwa wa,
    bí ọ̀wààrà òjò lórí koríko,
tí kò gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn
    tàbí kò dúró de àwọn ọmọ ènìyàn.
Ìyókù Jakọbu yóò sì wà láàrín àwọn aláìkọlà
    ní àárín àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn,
bí i kìnnìún láàrín àwọn ẹranko inú igbó,
    bí i ọmọ kìnnìún láàrín agbo àgùntàn,
èyí tí ó máa ń fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
    tí ó sì máa ń tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀,
    tí kò sì ṣí ẹnìkan tí ó lè gbà á là.
A ó gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀,
    gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sì ni a ó parun.

10 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,

“Èmi yóò pa àwọn ẹṣin rẹ̀ run kúrò láàrín rẹ
    èmi yóò sì pa àwọn kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ run.
11 Èmi yóò sì pa ilẹ̀ ìlú ńlá rẹ̀ run,
    èmi ó sì fa gbogbo ibi gíga rẹ̀ ya.
12 Èmi yóò gé ìwà àjẹ́ kúrò lọ́wọ́ rẹ̀,
    ìwọ kì yóò sì ní aláfọ̀ṣẹ mọ́.
13 Èmi yóò pa àwọn ère fínfín rẹ̀ run,
    àti ọwọ́n rẹ̀ kúrò láàrín rẹ̀;
ìwọ kì yóò sì le è foríbalẹ̀
    fún iṣẹ́ ọwọ́ rẹ mọ́.
14 Èmi yóò fa ère Aṣerah tu kúrò láàrín rẹ̀,
    èmi yóò sì pa ìlú ńlá rẹ̀ run.
15 Èmi yóò gbẹ̀san ní ìbínú àti ìrunú
    lórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò ti tẹríba fún mi.”

Ọlọ́run pe Israẹli níjà

Ẹ fi etí sí ohun tí Olúwa wí:

“Dìde dúró, bẹ ẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ rẹ níwájú òkè ńlá;
    sì jẹ́ kí àwọn òkè kéékèèkéé gbọ́ ohun tí ó fẹ́ wí.

“Gbọ́, ìwọ òkè ńlá, ẹ̀sùn Olúwa;
    gbọ́, ìwọ ìpìlẹ̀ ilé ayérayé.
Nítorí Olúwa ń bá àwọn ènìyàn rẹ̀ wíjọ́;
    òun yóò sì bá Israẹli rojọ́.

“Ẹ̀yin ènìyàn mi, kí ni mo ṣe fún yín?
    Àti nínú kí ni mo ti dá yin lágara? Dá mi lóhùn.
Nítorí èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá,
    mo sì rà yín padà láti ilẹ̀ ẹrú wá.
Mo rán Mose láti darí yín,
    bákan náà mo rán Aaroni àti Miriamu síwájú rẹ̀.
Ìwọ ènìyàn mi,
    rántí ohun tí Balaki ọba Moabu gbèrò
    àti ohun tí Balaamu ọmọ Beori dáhùn.
Rántí ìrìnàjò rẹ̀ láti Ṣittimu dé Gilgali,
    kí ìwọ ba le mọ òdodo Olúwa.”

Kí ni èmi yóò ha mú wá síwájú Olúwa
    tí èmi ó fi tẹ ara mi ba níwájú Ọlọ́run gíga?
Kí èmi ha wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,
    pẹ̀lú ọmọ màlúù ọlọ́dún kan?
Ǹjẹ́ Olúwa yóò ní inú dídùn sí ẹgbẹgbàarùn-ún àgbò,
    tàbí sí ẹgbẹgbàarùn-ún ìṣàn òróró?
Èmi yóò ha fi àkọ́bí mi sílẹ̀ fún ìré-òfin-kọjá mi,
    èso inú ara mi fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkàn mi?
Ó ti fihàn ọ́, ìwọ ènìyàn, ohun tí ó dára,
    àti ohun tí Olúwa ń béèrè lọ́wọ́ rẹ?
Bí kò ṣe láti ṣe òtítọ́, kí o sì fẹ́ràn àánú,
    àti kí o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli àti ìjìyà wọn

Gbọ́! Ohùn Olúwa kígbe sí ìlú ńlá náà,
    láti jẹ ọlọ́gbọ́n ni láti bẹ̀rù orúkọ rẹ.
    “Ẹ kíyèsi ọ̀pá rẹ̀ gbọ́ ọ̀pá àti Ẹni náà tí ó yàn án
10 Ǹjẹ́ ìṣúra ìwà búburú ha wà
    ní ilé ènìyàn búburú síbẹ̀,
    àti òṣùwọ̀n àìkún tí ó jẹ́ ohun ìbínú?
11 Ǹjẹ́ èmi ha lè kà wọ́n sí mímọ́
    pẹ̀lú òṣùwọ̀n búburú,
    pẹ̀lú àpò òṣùwọ̀n ẹ̀tàn?
12 Àwọn ọlọ́rọ̀ inú rẹ̀ kún fún ìwà ipá;
    àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ ti ọ̀rọ̀ èké
    àti ahọ́n wọn ń sọ ẹ̀tàn?
13 Nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ ṣàìsàn ní lílù ọ́,
    láti sọ ọ́ dahoro nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
14 Ìwọ yóò jẹun ṣùgbọ́n kì yóò yó;
    ìyàn yóò wà láàrín rẹ;
Ìwọ yóò kó pamọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò lò láìléwu,
    nítorí ohun tí ìwọ kò pamọ́ ni èmi yóò fi fún idà.
15 Ìwọ yóò gbìn ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò kórè
    ìwọ yóò tẹ olifi,
ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò fi òróró rẹ̀ kún ara rẹ;
    ìwọ yóò tẹ èso àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò mu wáìnì.
16 Nítorí tí ìwọ ti pa òfin Omri mọ́,
    àti gbogbo iṣẹ́ ilé Ahabu,
    tí ó sì ti tẹ̀lé ìmọ̀ràn wọn,
nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ fún ìparun
    àti àwọn ènìyàn rẹ fún ìfiṣe ẹlẹ́yà;
    ìwọ yóò sì ru ẹ̀gàn àwọn ènìyàn mi.”

Ìrora Israẹli

Ègbé ni fún mi!
Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ,
    ìpèsè ọgbà àjàrà;
kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ,
    kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà,
    kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́;
gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀,
    olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú;
    àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn,
àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀
    alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́,
    gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún,
    ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ.
Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé,
    àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò.
    Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́;
    ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan.
Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni
    tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
(I)Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀,
    ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀,
aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀,
    ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.

Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa,
    Èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi;
    Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.

Israẹli yóò dìde

Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi;
    Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde.
Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn
    Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i,
    Èmi yóò faradà ìbínú Olúwa,
títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò,
    tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi.
Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀;
    èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
10 Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i
    ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé,
“Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?”
    Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀;
nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀
    bí ẹrẹ̀ òpópó.

11 Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé,
    ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
12 Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ
    láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti
àní láti Ejibiti dé Eufurate
    láti Òkun dé Òkun
    àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
13 Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀,
    nítorí èso ìwà wọn.

Àdúrà àti ìyìn

14 Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ,
    èyí tí ó ń dágbé nínú igbó
ní àárín Karmeli;
    Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi
    bí ọjọ́ ìgbàanì.

15 “Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá,
    ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”

16 Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n,
    nínú gbogbo agbára wọn.
Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn,
    etí wọn yóò sì di.
17 Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò,
    wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló.
Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa,
    wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
18 Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀,
    ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì,
    tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀?
Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé
    nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
19 Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa;
    òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀,
    yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
20 (J)Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu
    ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu,
bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa
    láti ọjọ́ ìgbàanì.

Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.

Ìbínú Olúwa sí Ninefe

Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san.
    Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú
Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀,
    Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀
(K)Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára;
    Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà.
Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì,
    Ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ó bá Òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ;
    Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ.
Baṣani àti Karmeli sì rọ,
    Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀,
    àwọn òkè kéékèèkéé sì di yíyọ́,
ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀,
    àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀?
    Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀?
Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná;
    àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.

Rere ni Olúwa,
    òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
    Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá
ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin;
    òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.

Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa?
    Òun yóò fi òpin sí i,
    ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì
10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú
    wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn
    a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ
11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá
    tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa
    ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.

12 Báyìí ni Olúwa wí:

“Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye,
    Ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀,
nígbà tí òun ó bá kọjá.
    Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójú mọ́.
13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ
    èmi yóò já ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”

14 Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe:
    “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́,
Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run
    tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ.
Èmi yóò wa ibojì rẹ,
    nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”

15 (L)Wò ó, lórí àwọn òkè,
    àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá,
    ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà,
Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́,
    kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ.
Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́;
    wọn yóò sì parun pátápátá.

Ìṣubú Ninefe

Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe
    pa ilé ìṣọ́ mọ́,
    ṣọ́ ọ̀nà náà
    di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le,
    múra gírí.

Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò
    gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli
bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run,
    tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.

Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa;
    àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó.
Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná
    ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán;
    igi firi ni a ó sì mì tìtì.
Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà,
    wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro.
Wọn sì dàbí ètùfù iná;
    tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.

Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀;
    síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn;
wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀,
    a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀,
    a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀
    ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ.
A ó sì mú un gòkè wá
    àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà,
    wọn a sì máa lu àyà wọn.
Ninefe dàbí adágún omi,
    tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ.
“Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe,
    ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
“Ẹ kó ìkógun fàdákà!
    Ẹ kó ìkógun wúrà!
Ìṣúra wọn ti kò lópin náà,
    àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
10 Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro:
    ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn,
    ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́
    àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.

11 Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà
    àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún,
níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn,
    àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù
12 Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀,
    ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀,
Ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀
    àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.

13 “Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín,
    idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run.
    Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé
Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ
    ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”

A fi Ninefe bú

Ègbé ni fún ìlú ẹ̀jẹ̀ nì,
    gbogbo rẹ̀ kún fún èké,
ó kún fún olè,
    ìjẹ kò kúrò!
Ariwo pàṣán àti ariwo
    kíkùn kẹ̀kẹ́ ogun
àti jíjó ẹṣin
    àti gbígbọn kẹ̀kẹ́ ogun jìgìjìgì!
Ológun orí ẹṣin ń fi ìgbónára
    ju idà wọn mọ̀nàmọ́ná
    ọ̀kọ̀ rẹ̀ ti ń dán yanran sí òkè!
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ si ní àwọn ẹni tí a pa,
    àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú;
òkú kò sì ni òpin;
    àwọn ènìyàn sì ń kọsẹ̀ lára àwọn òkú.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ panṣágà
    àgbèrè tí ó rójú rere gbà,
Ìyá àjẹ́ tí ó ṣọ́ àwọn orílẹ̀-èdè di ẹrú
    nípa àgbèrè rẹ̀
    àti àwọn ìdílé nípa ìṣe àjẹ́ rẹ̀.

“Èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
    “Èmi ó si ká aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ ní ojú rẹ,
Èmi yóò sì fi ìhòhò rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè
    àti ìtìjú rẹ̀ han àwọn ilẹ̀ ọba.
Èmi yóò da ẹ̀gbin tí ó ni ìríra sí ọ ní ara,
    èmi yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́,
    èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà.
Gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé,
    ‘Ninefe ṣòfò: Ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’
    Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”

Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tebesi lọ,
    èyí tí ó wà ní ibi odò, Naili
    tí omi sì yí káàkiri?
Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀,
    omi si jẹ́ odi rẹ̀.
Etiopia àti Ejibiti ni agbára rẹ, kò sí ní òpin;
    Puti àti Libia ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùn
    o sì lọ sí oko ẹrú.
Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀
    ní orí ìta gbogbo ìgboro.
Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin,
    gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè
11 Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara;
    a ó sì fi ọ́ pamọ́
    ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.

12 Gbogbo ilé ìṣọ́ agbára rẹ yóò dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́
    pẹ̀lú àkọ́pọ́n èso wọn;
Nígbà tí wọ́n bá ń gbọ̀n wọ́n,
    ọ̀pọ̀tọ́ yóò sì bọ́ sí ẹnu àwọn ọ̀jẹun.
13 Kíyèsi gbogbo àwọn jagunjagun!
    Obìnrin ni gbogbo wọn.
Ojú ibodè rẹ ní a ó ṣí sílẹ̀ gbagada,
    fún àwọn ọ̀tá rẹ;
    iná yóò jó ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn ibodè rẹ.

14 Pọn omi nítorí ìhámọ́,
    mú ilé ìṣọ́ rẹ lágbára sí i
wọ inú amọ̀
    kí o sì tẹ erùpẹ̀,
    kí ó sì tún ibi tí a ti ń sun bíríkì-amọ̀ ṣe kí ó le.
15 Níbẹ̀ ni iná yóò ti jó ọ́ run;
    idà yóò sì ké ọ kúrò,
    yóò sì jẹ ọ́ bí i kòkòrò,
yóò sì sọ ara rẹ̀ di púpọ̀ bí i tata,
    àní, di púpọ̀ bí eṣú!
16 Ìwọ ti sọ àwọn oníṣòwò rẹ di púpọ̀
    títí wọn yóò fi pọ̀ ju ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ
Ṣùgbọ́n bi eṣú ni wọn yóò sọ ilẹ̀ náà di ahoro, wọn yóò sì fò lọ.
17 Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú,
    àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá,
    èyí tí ń dó sínú ọgbà ni ọjọ́ òtútù,
ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn jáde, wọ́n sálọ
    ẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.

18 Ìwọ ọba Asiria,
    àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ ń tòògbé;
àwọn ọlọ́lá rẹ dùbúlẹ̀ láti sinmi.
    Àwọn ènìyàn rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè ńlá,
    tí ẹnikẹ́ni kò sì kó wọn jọ.
19 Kò sì sí ohun tí ó lè wo ọgbẹ́ ẹ̀ rẹ sàn;
    ọgbẹ́ rẹ kún fún ìrora
Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ ìròyìn rẹ
    yóò pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,
nítorí ta ni kò ní pín nínú
    ìwà búburú rẹ ti kò ti lópin.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.